Smiley face

Orin òwe, orín ọtẹ, orín Sai Buhari tí gba gbogbo Bauchi báyìí

Ni ìpínlẹ̀ Bauchi wọn kó Buhari jẹ́ bí "abinci".

Lọja Satide to kọjá yìí ni èrò bí èrò mecca tú jáde láti yọ ayọ̀ ọdún mẹta tí Sai Baba ti gorí aleefa gẹ́gẹ́ bí aare ilẹ̀ Nàìjíríà.

Bí wọn ṣe kọrin òwe bẹẹ ni wọn kọrin koriya fún ọkọ Aisha. Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí oniroyin kan, Ibrahim Tijani láti Bogoro ni ìpínlẹ̀ Bauchi ṣe ja mi tán.

Ó ní "Olayemi Oniroyin, má mà dá àwọn eléyìí lóun, àwọn tí ayé wọn ti sá málámálá". Tijani ti ń sọ Hausa lo tún fi ọba Ọlọ́run Allah seri wí pé, ìṣe owó tí àwọn èrò yìí gbà ni wọn ṣe.

Ó sì tún fi dá wa lójú wí pe kii se ipínlẹ̀ Bauchi nìkan ni eléyìí yóò ti wáyé. Tijani tún ṣàlàyé wí pé, ninu ijoba ọdún mẹta Buhari, ó bá ní lọkan je wí pé a ko ri ohunkóhun náwó sì gẹ́gẹ́ bí àṣeyọrí.

Ṣùgbọ́n nínú ọ̀rọ̀ Tinubu lọjọ tí ń ṣe ojo ìbí, ó ni a kò lè fojú pa àṣeyọrí Buhari rẹ, pàápàá jù lọ tí a bá ń sọ nípa ifọlumọ kúrò lọ́wọ́ jegudujẹra.

Ṣùgbọ́n ní Satide to kọjá yìí, 31/03 /2018, wọn gbé arọ tí kò lè rìn kọrun níbi tí àwọn èrò tí ń pariwo wí pé, Buhari ni àwọn tún fẹ lodun 2019.

Share on Google Plus

About Olayemi Oniroyin

0 comments:

Post a Comment